Ìtúpalẹ̀ Àṣàyàn Àkóónú Oríkì Ilẹ̀ Yorùbá

Authors

  • Ìlúfóyè Fáwọlé Òjó, Ph.D Adeyemi Federal University of Education, Ondo Author
  • Mercy Ayo FASEHUN, Ph.D Author

Keywords:

Oríkì, Oríkì-orílẹ̀, Àwùjọ Yorùbá, Ìtúpalẹ̀, Àṣàyàn

Abstract

Oríkì jẹ́ ẹ̀yà lítíréṣọ̀ kan tí ó jinlẹ̀ púpọ nínú gbogbo lítíréṣọ̀ alohùn Yorùbá  nítorí pé ó jẹ́ orísun ìtàn, ẹ̀sìn, ìṣe, ìṣesí, ìfẹ́, èèwọ̀, iṣẹ́ ìran, àbùdá ìrísí àti ìwà ìran kan. Yàtọ̀ sí èyí, oríkì kò mọ ní ti ẹ̀dá ènìyàn nìkan, Olódùmarè, àwọn òrìṣà àkúnlẹ̀bọ, àwọn ẹranko àti ẹyẹ náà ní oríkì tiwọn.  Àwọn nǹkan mìíràn bí kòkòrò, òkè, ilẹ̀, odò, igi, ewé, àwọn oúnjẹ ìbílẹ̀, èso, àìsàn, àrùn àti àwọn nǹkan mìíràn náà ní oríkì tiwọn lọ́kan-ò-jọ̀kan. Èyí fi hàn wá pé oríkì gbòòrò púpọ̀ àti pé kò fẹ́rẹ̀ sí ohun tí ó wà lórílẹ̀ ayé yìí tí Olódùmarè dá tí kò ní oríkì tirẹ̀. Oríkì, pàápàá oríkì orìlẹ̀ máa ń farahàn nínú gbogbo ìṣèré àwọn akéwì tàbí apohùn Yorùbá. Ìṣàmúlò oríkì nínú ìṣèré wọn máa ń fi wọ́n hàn gẹ́gẹ́ bí akéwì tó dáńtọ́ láwùjọ Yorùbá. Nínú iṣẹ́ ìwádìí yìí, a wo ìtumọ̀ àti àbùdá oríkì Yorùbá. A tún ṣe ìtúpalẹ̀ àkóónú àṣàyàn oríkì tí ó tọ́ka sí àṣá, ẹ̀sìn, ìṣe, èèwọ̀, ìtàn, ẹbí ohun tí ó jẹ́ àléébù àwọn ìran wọ̀nyí. Àbájáde iṣẹ́ ìwádìí yìí fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé oríkì máa ń roni, àlàjẹ́ a sì máa ro ènìyàn. Oríkì a máa mù orí ẹni wú, ó máa fúnni ní ìgboyà pẹ̀lú ìmọ̀lára, ó máa ń júwe orírun ẹni, ó sì máa ń fini lọ́kànbalẹ̀ pé ojúlówó ọmọ ìran báyìí ni irú ẹni bẹ́ẹ̀ jẹ́. Ọ̀kan lára àwọn ogún ìní ìran kọ̀ọ́kan ní ilẹ̀ Yorùbá ni oríkì jẹ́, a kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó parun.   

Author Biography

  • Ìlúfóyè Fáwọlé Òjó, Ph.D, Adeyemi Federal University of Education, Ondo

    Ìlúfóyè Fáwọlé ÒJÓ, PhD  a Senior Lecturer in the Department of Yorùbá, Adéyẹmí Federal University of Education, Oǹdó .

    His research interest, teaching and publications are in the areas of Yorùbá Oral Literature, Folklore, Yorùbá Culture, Yorùbá Studies and Stylistics. He holds B. A. (Ed) Yorùbá at Adéyẹmí College of Education, (now Adéyemí Federal University of Education, Oǹdó) affiliated  to Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ University, Ilé-Ifẹ̀ in 1993, M. A. in Yorùbá Literature and Culture at  Lagos State University, Ojo, Lagos in 2004. He also has M. A   Yorùbá Language and Literature in 2016 and PhD in Yorùbá Language and Literature from Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ University, Ilé-Ifẹ̀, Nigeria  in 2020. He is a member of Ẹgbẹ́-Onímọ̀ Èdè Yorùbá (Yorùbá Studies Association of Nigeria (YSAN) and Ẹgbẹ́ Ọ̀mọ̀ràn Èdè Yorùbá (Association of Yorùbá Language Scholars) (ASSYLAS).

    He has published articles in various reputable journals both local and international. He has co-authored text books in Yorùbá oral literature, edited Yorùbá books, contributed chapters to books and also attended conferences in both local and international conferences with papers presented. He has co-authored Yorùbá reading text books for both primary and secondary schools. All these works remain a good reference material for both teachers and students in primary schools, secondary schools and tertiary institutions where Yorùbá is being taught.

Downloads

Published

2025-09-22