Ondo Journal of Art, OJA Adeyemi University, Adeyemi Federal University of Education Ondo, Nigerian art journal, African art and culture research, Fine and applied arts journal Nigeria, Art education in Nigeria, Art and aesthetics publications, Contemporary African art studies, Visual arts journal Nigeria

Ìlò Àwàdà fún Yíyanjú Ìṣòro Ìbára-ẹni-gbé-pọ̀ Ajẹmọ́dìílé Gẹ́gẹ́ BIí Ó Ṣe Hàn Nínú Àwọn Àṣàyàn Ìwé Eré-Onítàn Yorùbá

Authors
  • Grace Oluwakemi Adefowope

    Our Lady of Apostles Secondary School, Ijebu-Ode

    Author

Keywords:
Àwàdà,, Ìbára-ẹni-gbé-pọ̀, Ìkóra-ẹni-níjàánu, Ìṣòro, Ìdílé
Abstract

Àṣamọ̀
Ohun tí ó bí iṣẹ́ ìwádìí yìí ni àwọn ìṣòro tí ó ń kojú ìbára-ẹni-gbé-pọ̀ nínú ètò ìdílé àti ipa tí àwọn ìṣòro wọ̀nyí ní lórí àwùjọ. Lára àwọn ìṣòro wọ̀nyí ni ìfojútẹ́ńbẹ́lú-ẹni, ìfẹ̀mí-òkùnkùn báni jà, àìnímọ̀ọ́tótó, ìjà, ìmẹ́lẹ́, àìnítẹríba,àìlẹ́kọ̀ọ́-iléàti àṣìlò ọmọ-ọ̀dọ̀.Èròńgbà iṣẹ́ ìwádìí yìí ni láti wò bí ìlò àwàdà ṣe lè yanjú ìṣòro ìbára-ẹni-gbé-pọ̀ ajẹmọ́dìílé nípa ìfòótọ́-ọ̀rọ̀ gún aṣebi lára nípasẹ̀ ẹ̀rín rírín, kí ó lè jẹ́ àríkọ́gbọ́n fún ẹlòmíràn. Ọgbọ́n iwádìí tí iṣẹ́ yìí tọ̀ ni ṣíṣe ìtúpalẹ̀ kíkún lórí àkóónú àṣàyàn ìwéeré-onítàn méjì, ìyẹnÌyá Yáádì tí Dòsùmú kọ àti Nítorí Owó tí Ìṣọ̀lá kọ láti wo bí àwọn òǹkọ̀wé ṣe lo àwàdàfúnyíyanjú àwọn ìṣòro ìbára-ẹni-gbé-pọ̀ ajẹmọ́dìílé.Tíọ́rì ìfojú-ìmọ̀-ìbára-ẹni-gbé-pọ̀-wò-lítíréṣọ̀ ni ọ̀pákùtẹ̀lẹ̀ tí iṣẹ́ yìí rọ̀ mọ́ nítorí pé láti inú àwùjọ ni ìlò àwàdà ti máa ń jẹ yọ.Iṣẹ́ ìwádìí yìí ríi pé lára okùnfà ìṣòroìbára ẹni-gbé-pọ̀ ajẹmọ́dìílé ni àìnífẹ̀ẹ́, àìnísùúrù, àìkọ́mọ-lẹ́kọ̀ọ́-ilé tó àtiàìníṣẹ́. Iṣẹ́ ìwádìíyìí gbà pé ìlò àwàdà kó ipa ribiribi nínú yíyanjú ìṣòro ajẹmọ́dìílé dé àyè kan gẹ́gẹ́ bí ó ṣe hàn nínú àwọn ìwé àmúlò. Ọ̀nà àbáyọ tíIṣẹ́ ìwádìíyìí dábàá ni pé àwùjọ fi àyè gba ìlò àwàdà gẹ́gẹ́ bíi ijánu fúnìwà ìbàjẹ́, kí ẹ̀mí ìkóra-ẹni-níjàánu lè fẹsẹ̀ múlẹ̀ síi nínú ìdílé, kí àwọn tí pẹ̀tẹ̀pẹ́tẹ̀ àwàdà bá ta sí lára gbìyànjúláti ṣe àtúnṣe.

References
Cover Image
Downloads
Published
2025-09-22
Section
Articles