ÒWE YORÙBÁ GẸ́GẸ́ BI ÌPÍNṢÍṢỌ̀RÍ Ẹ̀YÀ LÍTÍRÉṢỌ̀ ALOHÙN YORÙBÁ
- Authors
-
-
SA'ADU Taofiq Ph.D
Adeyemi Federal University of Education, Ondo.
Author
-
- Keywords:
- Òwe Yorùbá, Lítíréṣọ̀ alohùn, Tíọ́rì ìfìwádìí-sọ̀tumọ̀-ìṣẹ̀lẹ̀-àwùjọ
- Abstract
-
Àṣamọ̀
Àfojúsùn ìwádìí yìí ni àgbéyẹ̀wò òwe Yorùbá gẹ́gẹ́ bi ìpínṣíṣọ̀rí ẹ̀yà lítíréṣọ̀ alohùn Yorùbá. Iṣẹ́ yìí ṣe àkíyèsí pé, ọ̀pọ̀ ìwádìí tó wà nílẹ̀ tẹ́lẹ̀ lórí òwe ni kò fi bẹ́ẹ̀ kọbi-ara sí ẹ̀yà lítíréṣọ̀ alohùn Yorùbá tí a lè ka wọ́n sí. Àwọn onímọ̀ kan kà òwe sí èròjà lásán fún ewì alohùn Yorùbá. Ìwádìí yì gbìyànjú láti dí àlàfo yìí nípa ṣíṣe àgbéyẹ̀wò òwe láti ṣàlàyé àbùdá àti ìpínsíṣọ̀rí rẹ̀ nínú lítíréṣọ̀ alohùn Yorùbá. Ìlànà ìṣèwádìí méjì ni a ṣe àmúlò nínú iṣẹ́ yìí; àkọ́kọ́ ni ṣíṣe àkójọpọ̀ òwe Yorùbá láti inú ọ̀kan-ò-jọ̀kan ìmọ̀ ìgbé-ayé àwùjọ Yorùbá. Ọgbọ́n ìṣèwádìí kejì ni ṣíṣe àmúlò àwọn ìwé tí ó wúlò fún iṣẹ́ yìí, àwọn ìwé bíi, jọ́nà, átíkù àti orí ìtàkùn ayélujára. Àwọn àkójọ-èdè-fún-àyẹ̀wò yìí ni a fi tíọ́rì ìfìwádìí-sọ̀tumọ̀-ìṣẹ̀lẹ̀-àwùjọ (Sociological Hermeneutics) ṣe ìtúpalẹ̀ rẹ̀. Ìdí pàtàkì tí a fi ṣe àmúlò tíọ́rì yìí ni láti wo ìwúlò òwe pẹ̀lú iṣẹ́ tí wọ́n ń fi wọ́n ṣe nínú àgbékalẹ̀ ìhun àwùjọ. Àbájáde ìwádìí yìí fi hàn pé iṣẹ́ tí òwe ń ṣe ní àwùjọ Yorùbá kò kéré rárá, àtipé, bí a bá wo àbùdá òwe Yorùbá a ó rí i pé ó kọjá èròjà fún ẹ̀yà ewì alohùn Yorùbá kan lásán gẹ́gẹ́ bí àwọn onímọ̀ kan ti ṣe ṣe àlákalẹ̀ rẹ̀. Nípa wíwo iṣẹ́ pàtàkì tí à ń fi òwe ṣe ní àwùjọ àti títò òwe Yorùbá sí ààyè tó yẹ nínú ìpínsíṣọ̀rí lítíréṣọ̀ Alohùn Yorùbá, a lérò pé ìwádìí yìí yóò rí ohun tuntutn fi kún ìmọ̀ nínú iṣẹ́ akadá.
- Author Biography
- References
- Cover Image
-
- Downloads
- Published
- 2026-04-30
- Section
- Articles